Orí Kẹẹ̀sán

1 Jésù sì wi fún wọn pé, "Lóòtọ́ọ́ ni mo wí fún yín, ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú yín tí ó dúró níhìńyí ní kì yíò rí ikú kí wọ́n tó rí ìjọba ọlọ́run tí yíò dè pẹ̀lú agbára." 2 Lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́fà, Jésù mú Pétérù àti Jákọ́bù àtiJòhánù pẹ̀lú Rẹ̀ lọ sórí òkè gíga, wọ́n dáwà níbẹ̀. A sì paá láradà níwájú wọn. 3 Aṣọ Rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ síí tàn bí i mọ̀nàmọ́ná, ó funfun bí ọṣẹ ìfọṣọ ayé kan ìbá fi fọ̀ ọ́ lọ. 4 Lẹ́hìn náà, Èlíjà àti Mósè fara hàn wọ́n, wọ́n sì ń bá Jésù sọ̀rọ̀. Pétérù dáhùn ó sì wí fún Jésù pé, 5 "Olùkọ́ni, ó dára fún wa láti máa gbé ibíyìí, nítorínà, Ẹ jẹ́ ká kọ́ ilé'gbe mẹ́ta, ọ̀kan fún ọ, ọ̀kan fún Mósè, àti ọ̀kan fún Èlíjà." 6 (Nítorí Pétérù kò mọ ohun tí yíò sọ, nítorí ẹ̀rù bà wọ́n gidigidi) 7 Àwọ̀ sánmọ́ sì ṣíjibòwọ́n mọ́lẹ̀. Lẹ́sẹ̀kẹṣè, ohùn kan jáde wá láti inú àwọ̀ọsánmọ̀ wá wípé, "Èyí ni àyànfẹ́ ọmọ mi, ẹ máa gbọ́ tirẹ̀." 8 Bí wọ́n ti wò àyíká wọn, wọn kò rí ẹnìkankan pẹ̀lú wọn mọ́, bíkòṣe Jésù nìkan. 9 Bí wọ́n ti ń ti orí òkè sọ̀kalẹ̀, Jésù pàṣẹ fún wọn láti máṣe sọ ohun tí wọ́n ti rí fún ẹnikẹ́ni, títí tí àwọn ọmọ ènìyán yíò fi jí dìde láàrin àwọn òku. 10 Nítorínà, wọ́n pa ọ̀rọ̀ náà mọ́ láàrin ara wọn, ṣùgbọ́n wọ́n ń jíròrò láàrin ara wọn nípa ohun tí "jíjí dìde kúrò láàrin àwọn òku" túmọ̀ sí. 11 Àwọn ọmọ ẹ̀yìn bi Jésù léèrè pé, "Èéṣe tí àwọn akọ̀wé fi ṣọ wípé Èlíjà ni ó gbọ́dọ̀ kọ́kọ́ wá."? 12 Jésù wí fún wọn pé, "Èlíjà ti kọ́kọ́ wá ná láti mún ohungbogbo padàbòsípò.Èéṣe tí a wá fi kọ̀wé rẹ̀ pé Ọmọ ènìyàn gbọ́dọ́ jìyà ohun púpọ̀ kí á sì se Ṣé bíi ẹni tí kòní láárii? 13 Ṣùgbọ́n èmi wí fún n yín pé Èlíjá ti wá ná, wọ́n sì seé ohun gbogbo tí ó wù wọ́n síi, gẹ́gẹ́ bí ìwé mímọ́ ti wí nípa rẹ̀." 14 Nígbàtí wọ́n dé ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn yókù, wọ́n sì rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ èrò yí wọn ká bẹ́ẹ̀ni àwọn akọ̀wé sì ń bá wọn wíjọ́. 15 Bí wọ́n ti rí Jésù, ẹnu ya ọ̀pọ̀lọpọ̀ èrò náà bẹ́ẹ̀ni wọ́n sáré pàdé rẹ̀ wọ́n sì kíi. 16 Ó bi àwọn ọmọ ẹ̀yìn Rẹ̀ wípé, "Kíni ẹ̀yin bá wọn se àríyànjiyàn síi?" 17 Ẹnìkan láàrín èrò sì dáhùn ó wípé, "Olùkó, mo mú ọmọ mi tọ̀ Ọ́ wá.Ẹ̀míkẹ́mìí kan ti jẹ́ kó ya odi 18 Ó má ń gbáa mú, á sì gbée sánlẹ̀, bẹ́ẹ̀ni ó má ń mú kí ó máa pòfóló, kí ó sì ma payín keke, òun á sì gan pa. Mo bẹ àwọn ọmọ ẹ̀yìn Rẹ kí wọ́n leèle jáde kúrò nínú rẹ̀ sùgbọ́n wọn kò leè ṣeé." 19 Ó sì wí fun wọn pé, "Ìran aláìgbàgbọ́, èmi ó ti bá n yín gbé pẹ́ tó? Èmi ó ti mú sùúrù pẹ́ tó fún n yín? Mú u wá fún mi.?" 20 Wọ́n mú ọmọkùnrin náà wá sọ́dọ̀ rẹ̀, nígbàtí ẹ̀mí náà rí Jésù, ó jẹ́ kí gììrì ki ọmọ náà lójijì. Ọmọkùnrin náà ṣubú lulẹ̀ ó sì ń pòfóló. 21 Jésù bá bi bàbá ọmọ náà, "Ó ti pẹ́ tó tí ti wà nírú ipò yìí?" Bàbá rẹ̀ dáhùn ówípé, "Láti ìgbà èwe rẹ̀ ni. Ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìgbà, 22 ó tilẹ̀ má n gbe jù sínú iná tàbí sínú omi láti paá lára nígbà míràn. Bí O bá le se ohun kóhun, sàánú fún wa kí o sì ràn wá lọ́wọ́." 23 Jésù wí fún pé, "Bí ìwọ bá nípá? Ohun gbogbo ni ṣíṣe fún àwọn tí ó gbàgbọ́." 24 Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, bàbá ọmọ náà kígbe sókè wípé, "Mo gbàgbọ́! Ran àìgbàgbọ́ mi lọ́wọ´." 25 Nígbàtí Jésù rí ọ̀pọ̀ èrò tó n wá sọ́dọ̀ rẹ̀, Ó bá ẹ̀mí àìmọ́ náà wí, ó wípé, "Ìwọ ẹ̀mí odi àti ìdití, mo pàṣẹ fún ọ, jáde kúrò lára rẹ̀ kí o má sì ṣe padà síbẹ̀ mọ́." 26 kígbe tòò ó sì jẹ́ kí gììrì ki ọmọ náà gidigidi, ó sì jáde kúrò lára rẹ̀. Ọmọkùnrin náà sì ń wò bíi ẹnití ó ti kú, tóbẹ̀ẹ̀ tí àwọn ènìyàn fi wí pé, "ó ti kú". 27 Sùgbọ́n Jésù gbá ọwọ́ ọmọ náà mú, Ó fàá sókè, ọmọ náà sì dìde dúró. 28 Nígbàtí Jésù sì wọlé wá, àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ bií ní ìkọ̀kọ̀ pé, "Èéṣe tí àwa kò fi le è lèe jáde." 29 Ó dáhùn ósì wí fún won pé, "Irú èyí kò le ṣééṣe bíkòṣe nípasẹ̀ àdúrá." 30 Wọ́n sì jáde lọ kúrò níbẹ̀, wọ́n gba agbègbè Gálílì lọ. Jésù kò fẹ́ kí ẹnìkankan kí ó mọ ibi tí àwọn wà, 31 nítorí tí Ó n kọ́ àwọn ọmọ ẹ̀yìn Rẹ̀. Ó sọ fún wọn wípé, "A ó fi Ọmọ Ènìyàn lé àwọn ènìyàn lọ́wọ́, wọn ó sì ṣe ikú pa Á. Lẹ́yìn ìgbà tí Ó bá kú tán, lẹ́yìn ọjọ́ kẹta yíò jí dìde , 32 Sùgbọ́n ọ̀rọ̀ tí ó n sọ yìí kò yé wọn, ẹ̀rù si n bà wọ́n láti bèèrè lọ́wọ́ Rẹ̀. 33 Lẹ́yìn náà ni wọ́n wá sí Kápánámù. Nígbàtí ó sì ti wọ sínú ilé kan, Ó biwọ́n léèrè pé, "Kíni ẹ̀yin n bá ara yín sọ lójú ọ̀nà.?" 34 Wọ́n sì dákẹ́ jẹ́ẹ́. Nítorítí wọ́n ti n ṣe àríyànjiyàn láàrin ara wọn níti ẹnití ó pọ̀jùlọ láàrin wọn. 35 Nígbàtí Ó jókòó, Ó pe àwọn méjìlá sí ọ̀dọ̀ ara rẹ̀ ó sì wí fún wọn pé, "bí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ se ẹni àkọ́kọ́, Oun ni yíò jẹ́ ẹni ìkẹyìn àti ìránsẹ́ gbogbo ènìyàn." 36 Ó mú ọmọ kékeré kan Ó sì fi sí ààrin wọn. Jésù gbé e lọ́wọ́ Rẹ̀ ó sì wí fún wọn pé, 37 "Ẹnikẹ́ni tí ó bá gba ọmọdé kékeré yìí ní orúko mi, ó gbà mí pẹ̀lú, bí ẹnikẹ́ni básì gbà mí, kò gba Èmi nìkan, sùgbọ́n ó gba Ẹni tí ó rán mi pẹ̀lú." 38 Johánù wí fún Un pé, "Àwá rí ẹnìkan tí ó n le àwọn ẹ̀mi àìmọ́ jáde ní orúkọ Rẹ̀, àwa si dáalẹ́kun, nítorí kò tọ̀wálẹ́yìn." 39 Ṣùgbọ́n Jésù wí fún pé, "ẹ máṣe dá wọn lẹ́kun nítorípé kò sí ẹnikẹ́ni tí yíò ṣe iṣẹ́ agbára ní orúkọ mi tí o jẹ́ sọ ohun búburú nípa mi." 40 Ẹnikẹ́ni tí kòba sè ìlòdì síwa, ó wà pẹ̀lú wa. 41 Ẹnikẹ́ni tí ó fi ife omi kékeré fún ni nítorí tí ó jẹ́ ti Kristi, lóòtítọ́ ni mo sọ fún yín, kì yó pàdánù èrè rẹ̀. 44 42 Ẹnikẹ́ni tí ó bá mú ọ̀kan nínú àwọn ọmọ kékeré tí o gbàgbọ́ nínú mi kọsẹ̀, ó sàn fun kí á so ọọlọ nlá mọ́-ọn lọ́rùn kí á sì sọọ́ sìnú òkun. 43 Bí ọwọ́ rẹ kan bá mú ọ kọsẹ̀, gée dànù. Ó sàn fún ọ láti wọ ìjọba ọ̀run bíi akéwọ́ jù kí o lọ sí ọ̀run àpáàdì pẹ̀lú ọwọ́ méjèèjì lọ, nínú iná àjóòkú. 45 Bí ẹsẹ̀ rẹ kan bá mú ọ kọsẹ̀ pẹ̀lú, gée sọnù. Nitorí ó sàn fún ọ láti wọ Ìjọba ọ̀run bíi akésẹ̀ jù fún ọ pẹ̀lú ẹsẹ̀ méjèèjì, kí á sì gbé ọ jù sínú iná ọ̀run àpáàdì lọ 46 47 Bí ojú rẹ kan bá mú ọ kọsẹ̀, yọọ́ dànù. Nítorí ó sàn fún ọ láti wọ Ìjọba ọ̀run pẹ̀lú ojú kan jù kí o ní ojú méjèèjì kí á sì gbe ọ sọ sínú iná ọ̀run àpáàdì, 48 níbití ìpáàrà wọn kììkú, bẹ́ẹ̀ni iná wọn kììkú. 49 Nítorí olúkúlùkù ni a o fi iyọ̀ mú dùn pẹ̀lú iná. 50 Iyọ̀ dára, ṣùgbọ́n bí iyọ̀ bá sọ adùn rẹ̀ nù, báwo ni a o ṣe mú dùn padà? Ẹní iyọ̀ láàrin ara yín, ki ẹ sì wà ní àlàáfsíà pẹ̀lú ara yín."