1
kí gbogbo ọkàn se ìgbọ́ràn sí aláṣẹ, nítori kò sí àṣẹ àfi èyí tí ó wá láti ọ̀dọ̀Ọlọ́run. Àṣẹ tí ó wà
láàyè lati yàn láti ọ̀dọ̀Ọlọ́run.
2
Nítorinà ẹni tí ó takò àṣẹ ta ko pípaṣẹ Ọlọ́run; àwọn tí ó tako o ni
yoo gba ìdájọ́ lórí ara wọn.
3
Nítorí àwọn olórí kìí se ẹ̀rùjẹ̀jẹ̀si iṣẹ́rere, ṣùgbọ́n sí iṣẹ́ibi. Àbì o ti se ìpinnu láti má bẹ̀rù àwọn tí ó wà ní àṣẹ? Se ohun tí ó dára, ìwọ yoo sí gba ìfọwọ́sí.
4
Nítorí ó jẹ́ ẹrú Ọlọ́run sí ọ fún rere. Ṣùgbọn tí o bá se búburú, bẹ̀rù; nítorí kìí gbé idà sókè lai ní ìdí. Nítorí ó jẹ́ ìránṣẹ́Ọlọ́run, olùgbẹ̀san ìbínú fún àwọn tí ó ṣiṣẹ́ibi.
5
Nítorína o gbọ́dọ̀gbọ́ràn, kì íṣe nítorí ibi, bíkòse paapa nítorí ẹ̀rí ọkàn.
6
Nítori ìdí èyí ìwọ yoo san owó ori pẹ́lú. Nítori aláṣẹ jẹ́ìránṣẹ́Ọlọ́run, tí ó tọ́jú ohun èyí nígbà gbogbo.
7
San fún oníkálùkù, ohun tí ó jẹ tirẹ́: owó orí fún ẹni ti owó óri tọ́sí; owó ìpẹ̀fún ẹni tí owó ìpẹ̀tọ́sí; ẹ̀rù fún ẹni tí ẹ̀rù tọ́sí; iyì fún ẹni tí iyì tọ́sí.
8
Máse jẹ ẹnìkẹ́ni ní ohunkóhun, àyàfi kí a nífẹ ara wa. Nítorí ẹni tí ó bá nífẹ́ẹ̀aládugbo rẹ̀ti pa òfin mọ́.
9
Ìwé òfin: "Máse se àgbàrè, máse pànìyàn, máse jalè, máse yí ènìyàn lọ́kàn padà", Ati bí òfin miran báwà pẹ̀lú, a kó wọn pọ̀nínú gbólóhùn yi pe: " Fẹ́ omonìkejì rẹ gẹ́gẹ́bí ara rẹ.
10
Ìfẹ́kì ńse ìjàmbá fún aládúgbo rẹẹ̀; nítorí naa, ìfẹ́ni àmúṣẹ òfin.
11
Nítorí ìdí èyí , ẹ mọ àkókò, pé ó ti tó àkòkó fún yín láti jí kúro ní ojú orun yín. Nítorí ìgbàlà wa ti súnmọ́ìtòsí ju ìgbà tí a kọ́kọ́gbàgbọ́lọ.
12
Alẹ́ti lọ síwájú, ọjọ́si ti ṣúnmọ́ìtòsí. Nítorínà ẹ jẹ́kí a gbé sí ẹ̀gbẹ́kan iṣẹ́òkuǹkùn, àti kí ẹ jẹ́kí a gbé ìhámọ́ra ìmọ́lẹ̀wọ̀.
13
Ẹ jẹ́kí a rin ìrìn tí ó bá ojú mu, gẹ́gẹ́bí ní ọjọ́, kì se gẹ́gẹ́bí ẹ̀gàn àjọyọ̀tàbi ìmutípara; kí a má sì se rìn ni ìbálòpọ̀àìkú tàbí nínú ìdálẹ́nu ìfẹ́kúfẹ́, ati láti jẹ owú.
14
Ṣùgbọ́n gbé Jésù krístì wọ̀, àti máse se ípèsè fún ara, sí igbòríyín fún ìfẹ́kúfẹ́ẹ̀.