Orí kẹrìnlá

1 Ó ku ọjọ́ méjì sí àjọ ìrékọjá àti àjọ àíwúkárà. Àwọn olórí àlúfà àti akọ̀wé ń ro bí wọn yí ò ti rora mú Jésù láì fura kí wọn sí pá. 2 Nítorí wón ń sọ wípé, "Kìí se nígbà ọdún, kí rúkèrúdò má baà sẹlẹ̀ láàrín àwọn ènìyàn. 3 Nígbàtí Jésù wà ní Bẹ́tánì ní ilé Símónì adẹ́tẹ̀, bí ó ti jókǒ ní tábílì, obìnrin kan tí ó ní ìgò alabástà òróró iyebíye, tí ó jẹ́ aláìlábáwọn nérdì. Ó fọ́ ìgò náà ó sì dàá si ní orí. 4 Ṣùgbọ́n àwọn kan ń bínú. Wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ láàrín ara wọn, wọn sì wípé, "Kí ni ìdí tí a se fi òróró yi sòfò? 5 A kò bá ti ta òróró ìkunra dídùn yí ní ọ̀dúńrún dénárì, kí á sí fún àwọn aláìní." Wọ́n sí bá obìnrin náà wí. 6 Ṣùgbọ́n Jesu wípé, "Ẹ jọ̀wọ́ rẹ̀. Kílódé tí ẹ̀yin fi ń ba a wí? Ó ti se ohun dídára fún mi. 7 Nígbà gbogbo ní ẹ̀yin ní tálákà pẹ̀lú yín, ẹ̀yin sì le se oore fún wọn nígbà tí ó bá wù yín, ṣùgbọ́n èmi ni ẹ̀yin kó ní nígbà gbogbo. 8 Ó ti ṣe èyí tí ó le ṣe: ó ti fi òróró kùn ara mi fún ìsìnkú mi. 9 Lótǐtó ni mo wí fun yín, níbikíbi tí a ó gbé wàásù ìhìnrere ní gbogbo aiyé, a ó sì sọ̀rọ̀ ohun tí obìnrín yǐ ṣe ní ìrántí rẹ̀. 10 Nígbànáà ni Júdásì Iskariotu, ọ̀kan nínú àwọn méjìlà, sì tọ̀ àwọn olóri àlúfà lọ láti fàá le wọn lọ́wọ́. 11 Nígbàtí àwọn olórí àlùfáà sì gbọ́ èyi, wọ́n yọ̀, wọ́n sì ṣe ìlérí láti fún n ní owó. Ó sì ń wá ọ̀nà láti fi lé wọn lọ́wọ́. 12 Ní ọjọ́ kínǐ àjọ àìwúkárà, nígbàtí wọ́n pa ẹran ìrékọjà, àwọn ọmọ ẹ̀yìn wí fún n pé, "Níbo ni ìwọ fẹ́ kí á lọ pèsè sílẹ̀, kí ìwọ́ kí ó le jẹ ìrékọjá. 13 Ó sì rán méjì nínú àwọn ọmọ ẹ̀yin ó sì wí fún wọn pé, "E lọ sí iń ìlú, okùnrin tí ń ru 777 omi yíò pàde yín. Ẹ tẹ̀lẹ́ e. 14 NÍbití ó bá ti wọlé, ẹ tẹ̀lé e kí ẹ sì wí fún onílé wípé, 'Olùkọ́ni wípé, "NÍbo ni yàrá ìgbàlejò tí èmi yíò ti jẹ ìrékọjá pẹ̀lú àwọn ọmọ èyìn mi?" 15 Ò n ó sì fi gbọ̀ngàn ńlá kan tí a ti se lọ́sọ̌ lókè hàn yín tí a ti pèsè sílè. Níbẹ̀ ni kí ẹ̀yin kí ó pèsẹ̀ sílẹ̀ fún wa. 16 Àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ sì jáde lọ sí ìlú. Wọ́n sì rí i gẹ́gẹ́ bí ó ti sọ fún wọn, wọ́n sì pèsè ìrékọjá sílẹ̀. 17 Nígbàtí alẹ́ lẹ́, ó wá pẹ̀lú àwọn méjìlá. 18 Bí wọ́n sì ti jókǒ tí wọ́n ń jẹun, Jésù wípé, "Lõtọ ni mo wí fún n yín, ọ̀kan nínú yín tí ó ń bá mi jẹun yíò fi mí hàn. 19 Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní kãnú gidigidi, wọ́n sì ń bi ra wọn léérè lẽre lọ́kọ̃kan wípé, "Èmi ni bí? 20 Jésù sí dáhùn ó sì wí fún wọn pé, "Ọ̀kan nínú àwọn méjìlá, tí ó ń tọwọ́ bọ̀ inú àwo pẹ̀lu mi. 21 Nítòótọ́ Ọmọ ènìyàn yíò lọ bí a ti kọ̀wé nípa tirẹ̀. Ṣùgbọ́n ègbé ni fún ọkùnrin nâ tí yíò jé sábàbí ìdàlè Ọmọ ènìyàn! ìbá sàn fún ọkùnrin náà tí a kò bá bí sáyé rárá. 22 Bí wọ́n sì ti ń jẹun, Jésù mú àkàrà, ó sì súre, ó sì pínn. Ó sì fifún wọn ó wípé, "Gba èyí. Èyí ni ara mi. 23 Ó sì gbé àgò, ó dúpẹ́, ó sì fifún wọn, gbogbo wọ́n sì mu nínú rẹ̀. 24 Ó wí fún wọn pé, "Èyí ni ẹ̀jẹ̀ mi ti májẹ̀mú, tí a ta sílẹ̀ fún ọ̀pọ èniyàn. 25 Lõtọ ni mo wí fu]n n yín, èmi kì yíò mu nínú èso àjàrà mọ́, títí yíò fi di ọjọ́ nà nígbàtí èmi ó muú ní titun ní ìjọba Ọlọ́run 26 Nígbàtí wọ́n ti kọ orin kan, wọ́n jáde lọ sí orí òkè Òlìfí. 27 Jésu wí fún wọn pé, " Gbogbo yín ni yíò kọsẹ̀, nítorítí a ti kọ̀wé rẹ̀ pé, 'Èmi ó lù olùṣọ́ àgùntàn agbo agùntàn yíò sì túká. 28 Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ìgbà tí mo bá jí dìde, èmi ó ṣájúu yín lọ sí Galili. 29 Peteru wí fún u pé, "Bí gbogbo ènìyàn tilẹ̀ kọsẹ̀, èmi kì yó kọsè." 30 Jésù wí fún u pé, "Lõtọ ni mo wí fún ọ, lásǎlẹ́ yi, kí àkùkọ kí ó tó kọ nígbà méjì, ìwọ ô kò mí nígba mẹ́ta. 31 Ṣùgbọ́n Pétérù wípé, "Bí ó bá jẹ́ ti ikú pẹ̀lú rẹ, èmi kò ní sẹ́ ọ." Gbogbo wọ́n sì jẹ́jẹ̌ kannáà. 32 Wón sì wá sí ibi kàn tí à ńpè ní Gẹ́tsímánì, ó sì wí fún àwọn ọmọ èyìn rẹ̀ pé, "Ẹ jókǒ ní ìhín nígbàtí mo bá lọ gbàdúrà. 33 Ó sì mú Pétérù àti Jákọ́bù àti Jòhánù pẹ̀lú rẹ̀, ó sì bẹ̀rẹ́ sí ní ìrẹ̀wẹ̀sí ọkàn, ọkàn rẹ̀ sì dàrú gidigidi. 34 Ó sì wí fún wọn pé, "Ọkàn mi ńkãnu gidigidi, títí dé ojú ikú. Ẹ dúró níhǐn kí ẹ sì mã ṣọ́nà. 35 Jésù sí lọ síwájú díẹ̀, ó sì dojúbolẹ̀, ó sì gbàdúrà pé, bí ó bá se é se, kí wákàtí yìí ré kọjá kúrò lórí rẹ̀. 36 Ó wípé, "Abba, Bàbá, ohun gbogbo ni síse fún ọ. Mú ago yìí kúrò lórí mi. ṣùgbọ́n kì íṣe ti ìfẹ́ mi, bíkòse ti ìwọ." 37 Ó padà wá, ó sì rí wọn tí wón n sùn, ó sì wí fún Pétérù, "Símónì, ìwọ ń sùn bi? Ìwọ kò ha le sọ́nà fún wákàtí kan? 38 Ẹ máa sọ́nà kí e sì ma gbàdúrà kí ẹ̀yin kí ó má baà bọ́ sínú ìdánwò. Ẹ̀mí ń fẹ́ nítòótọ́, ṣùgbọ́n ó se àìlera fún ara." 39 Ó sì tún lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ wọn láti lọ gbàdúrà, ó sì tún lo ọ̀rọ̀ kanńà. 40 Ó sì tún bá wọn tí wọn ń sùn, nítorí tí ojú wọn wúwo wọn kó sí mọ ohun tí wọn yí ò sọ fún n. 41 Ó sì wá ní ìgbà kẹta ó sì wí fún wọn pé, " Sé ẹ̀yin sí n sùn ni? Ó ti tó! Wákàtí náà ti dé. Wò ó! Ati fi ọmọ ènìyàn lé àwọn ẹlẹ́sẹ̀ lọ́wọ́. 42 Ẹ dìde; ẹ jẹ́kí á lọ. Wó ò, ẹni tí yíò dà mí ti wà nítòsí." 43 Nígbàtí ó sì ń sọ̀rọ̀, Júdásì, ọ̀kan nínú àwọn méjìlá, dé, ọ̀pọ̀ ènìyàn sí wà pẹ̀lú rẹ̀ pẹ̀lú idà àti ọ̀kọ̀, láti ọ̀dọ̀ olórí àlúfà, àwọn akòwé, àti àwọn àgbà. 44 Ẹni tí yí ò dà á ti fún wọn ní àmì, wípé, " Ẹnikẹ́ni tí òun bá fi ẹnu kò ní ẹnu, òun ni. Ẹ mú u lọ." 45 Nígbàtí Júdásì sì dé, lójúkanńà ó tọ Jésù wá ó sì wípé, "Olùkọ́," ó sì fi ẹnu kò ó ní ẹnu. 46 Wọ́n sì mú u. 47 Ṣùgbọ́n ọ̀kan lára àwọn tí ó sún mọ́ wọn yọ idà rẹ̀ ó sì fi gé etí ọmọ-ọ̀dọ̀ olórí àlùfáà. 48 Jésù sì wí fún wọn pé, "Sé ẹ̀yin jáde wá gẹ́gẹ́ bí ẹni tí ó fé mú olè ni, pẹ̀lú idà àti ọ̀kọ̀ láti wá mú mi? 49 Nígbà tí mo wà pẹ̀lú yín nígbà gbogbo tí mo sì ń kọ́ọ yín ní témpílì, ẹ̀yin kò mú mi. Ṣùgbọ́n a se èyí kí á le mú ọ̀rọ̀-mímọ́ sẹ." 50 gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lu Jésù sì fií sílẹ̀ wọ́n sì sá lọ. 51 Ọmọkùnrin kan, tí ó fi asọ ọ̀gbọ̀ nìkan wé ara rẹ̀, sì ń tẹ̀lẹ́ Jésù. Nígbà tí àwọn ọkùnrin náà sì mú Jésù. 52 Ó fi asọ ọ̀gbọ̀ náà sílẹ̀, ó sì sá kúrò ní ìhòhò. 53 Wọ́n sì mú Jẹ́sù lọ ṣọ́dọ̀ olórí àlùfáà. Gbogbo àwọn olórí àlùfàà, àti àwọn àgbàgbà, àti àwọn akọ̀wé sì péjọ pẹ̀lú rẹ̀. 54 Pétérù sì n tọ̀ ọ́ lẹ́yìn ní òkèrè wọ̀ inú ilé, títí wọ́n fi dé àgbàlá olóri àlùfáà. Ó sì bá àwọn ẹ̀sọ́ jókǒ, tí wọ́n ń yáná. 55 Nígbànáà ni àwọn olórí àlùfá àti gbogbo àjọ ìgbìmọ̀ júù ńwá ẹ̀rí lòdì sí Jésù láti pa á. Wọn kò sì rí ohun kan. 56 Nítorípé ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó jẹ́rìí èké sí i, ṣùgbọ́n ohùn àwọn ẹlẹ́rǐ náà kò ṣọ̀kan. 57 Àwọn kan sì dìde, wọ́n ń jẹ́rǐ èké sí i; wọ́n wípé, 58 "Àwa gbọ́ tí ó ún sọ wípé, Èmi ó wó tẹ́mpìlì yí tí a fi ọwọ́ ṣe, ní wọ̀n ijọ́ mẹ́ta èmi ó sì kọ́ òmíràn tì a kò fi ọwọ́ se." 59 Síbẹ̀ ẹ̀rí wọn kò sọ̀kan. 60 Olórí àlùfáà sì dìde láarín wọn ó sì bi Jésù lêrè wípé, Ìwọ kò ní ìdáhùn bí, kíni ohun tí àwọn ènìyàn yín jẹ́rǐ lòdì sí ọ? 61 Ó sì dákẹ́, kò sì so ohunkóhun. Olórí àlùfáà sì bií lêrè wípé, "sé ìwọ ni Krístì ọmọ olùbùkún?" 62 Jésù wípé, "Èmi ni; ìwọ yíò sì rí ọmọ Ènìyàn nígbàtì ó bá jókǒ ní apá ọ̀tún agbára tí ó sì wà ní àwọ sánmọ̀." 63 Olórí àlùfáà sì fa asọ rẹ̀ ya ó sì wípe, "Sé a sì nílò ẹlẹ́rǐ bí? 64 Ẹ̀yín ti gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹ̀gàn náà. Kíni ìpinu yín? Gbogbo wọn sì kẹ́gàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bíi ẹni tí ó yẹ fún ikú. 65 Àwọn míràn bẹ̀rẹ̀ sí ní tutọ́ síi lára wọ́n sì bo ojú rẹ̀ wọ́n sì lû wọ́n wí fun pé, "sọtẹ́lẹ̀!" Àwọn ọmọ ogun sì mú wọ́n sì lùú. 66 Bí Pétérù sì ti wà ní ìsàlẹ̀ ní àafin, ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin olórí àlùfáà wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀. 67 Ó rí Pétérù tí ó ńyáná, ó tẹjú mọ́ ọ, ó sì wípe, ìwọ́ wà pẹ̀lú Jésù aráa Násárẹ́tì yí. 68 Ṣùgbọ́n ó sẹ́ ẹ, ó wípé, "Èmi kò mó bẹ́ẹ̀ni òye ohun tí ìwọ ńsọ kò tilẹ̀ yé mi." Ó sì jáde lọ sí àgbàlá. Àkùkọ sì kọ. 69 Ọmọbìnrin nǎ sì tún rí i, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ fún àwọn tí ó dúró níbẹ̀ pẹ́, "Ọ̀kan nínú wọn ni okùnrin yî. 70 Ó sì tún sẹ́ ẹ. Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, àwọn tí ó dúró níbẹ̀ tún wí fún Pétérù pé, "Lóòtọ́ ni, ọ̀kan nínú wọn ní ìwọ íṣe, nítorípé ará Gálílì ni ìwọ náà. 71 Ṣùgbọ́n ọ́ bẹ̀rẹ̀ sí ní fi ara rẹ̀ ré ó sì búra wípé, "Èmi kò mọ ọkùnrín yǐ tí ẹ̀ ń sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀." 72 Lójúkańnà àkùkọ sì kọ ní ìgbà kejì. Pétérù sí rántí ọ̀rọ̀ tí Jésù wí fún u pé: "Kí àkùkọ kí ó tó kọ lẹ́ẹ̀mejì , ìwọ ó sẹ́ mi lẹ́ẹ̀mẹta." ó bara jẹ́, ó sì sọkún.