Orí Kẹrinlá

1 Ní àkokò náà ni Hẹ́rọ́dù tẹ́trárkì gbọ́ ìròyìn nípa Jésù. 2 Ó sì ṣọ fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ wípé, "Èyí ni Jòhánù Baptístì; ó ti jí dì de láàrin àwọn òkú. Nítorínáà ni àwọn agbára wọ̀nyí ṣiṣẹ́ nínú rẹ̀. 3 Nítorítí Hẹ́rọ́dù ti mú Jòhánù, ó dè é, ó sì jú sí nú ẹ̀wọ̀n nítorí Hẹrọdíà, ìyàwó Phílípì arákùnrin rẹ̀. 4 Nítorítí Jòhánù wí fun pé, "Kò tọ̀nà fún ọ láti nì i gẹ́gẹ̀bí aya rẹ." 5 Hẹ́rọ́dù kò bá ti pá, sùgbọ́n o bẹ̀rù àwọn ènìyàn nítorípé wọ́n kà á sí wolǐ. 6 Sùgbọ́n nígbàtí ọjọ́ ìbí Hẹ́rọ́dù dé, ọmọbìnrin Hẹrọdíà sì jó láàrin èrò tí ó sì mú inú Hẹ́rọ́dù dùn. 7 Nítorínáà ó fi ìbúra ṣe ìlérí fún láti fún ní ohunkóhun tí ó bá bèèrè. 8 9 Lẹ́yìn tí ìyá rẹ̀ ti kọ́ kí ó wípé, "Fún mi ní orí Jòhánù Baptístì Inú sì bí ọba nítorí ìbúra rẹ̀ àti nítorí àwọn tí wọ́n bá a jókòó 10 Ó sì ní kí wọ́n bẹ́ orí Jòhánù nínú túbú. 11 A sì gbé orí Jòhánù wàá l'órí àwopọ̀kọ̀, a sì gbé fún ọmọ'bìnrin náà; ó sì gbe lọ fún ìya rẹ̀. 12 Àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ si wàá gbé òkú rè, wọ́n sì sín. Lẹ́yìn èy´, wọ́n sì lọ sọ fún Jésù. 13 Nígbàtí Jésù gbọ́ èyí, ó kúrò níbẹ̀ nínú ọkọ̀ ojú omi lọ sí nú ijù. Nígbàtí àwọn èrò gbọ́ èyí, wọ́n rìn tọ̀ ọ́ l'ẹ́ṣẹ̀. 14 Jésù sì jáde lọ, órí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn. Aanu wọ́n sì ṣe é, ó sì wo àwọn aláìsàn wọn lára dá. 15 Nígbàtí àṣalẹ de, àwọn ọmọ ẹ̀yìn sí tọ ọ wa, wọ́n sì wípé, " Ibi ijù ni èyí, àti wípé ọjọ́ ti kọjá. Rán àwọn ènìyàn náà jade, kí wọ́n le lọ sí ínu àwọn ìletò làti ra oúnje fún arawọn. 16 Sùgbọ́n Jesu wi fun pe, "Wọn ko nilo lati lọ sí ibi kankan. Ẹ fún wọn ní oun àti jẹ." 17 Wọn sì wí fún pe, "Awa kò ní ju àkàrà marun àtí ẹja meji." 18 Jesu sì wí fún wọn pé, "Ẹ kó wọn wá fún mi." 19 Jesu si paṣẹ fún àwọn ènìyàn náà joko lóri kórikó. Ó mú àkàrà marun náà pẹ̀lú ẹja méjì. Ó sì gbe oju rẹ̀ si oke ọrun, o sure, o si bù u, o fifún àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀, wọn sì fún àwọn ènìyàn náà. 20 Gbogbo sì jẹun, wọn sì yo. Nígbàtí wọn kó oun to ṣẹ kù, wọn kó apẹ̀rẹ̀ mejila ti ó kún. 21 Àwọn tí ó sì jẹun to ẹgbẹrún marun ọkùnrin láì ka àwọn obìnrin àti ọmọdé. 22 Lọ́gán ni ó mú àwọn ọmọ ẹ̀yìn wọ nú ọkọ̀ ojú omi àti pé kí wọ́n ṣáájú rẹ̀ lọ sí apákejì nígbàtí úun bá tú ìjọ àwọn ènìyàn ká. 23 Lẹ́yìn gbà tó ti tú ìjọ náà ká, Ó gorí òkè lọ tìkalára rẹ̀ láti lọ gbàdúrà. Nígbàtí àṣálẹ́ dé, òun nìkan ló wà níbẹ̀. 24 Sùgbọ́n nígbàtí ọkọ̀ ojú omi náà jìnà sí orí ilẹ̀ tí ń si ńbẹ láàrin adágún, tí ìrumi ǹ t´ síwá sẹ́hìn, nítorí afẹ́fẹ́ ṣe ọwọ́ òdì sí wọn. 25 Nigbati o di iṣọ kẹrin oru Jesu tọ wọn wa, ti o sin rìn lóri òkun. 26 Nígbàtí àwọn ọmọ ẹ̀yìn sí ri, ẹ̀rù ba wọn, wọn si wípé "Iwin ni", wọ́n si fi ìbẹ̀rù kígbe sókè. 27 Sùgbọ́n Jesu si wí fún wọn pe "Ẹ tuju ka! Emi ni! E ma bẹru." 28 30 Pétérù sì dáa lóhùn, ó ṣọ pé "Olúwa, bí o bájẹ́ ìwọ ni, pàṣẹ kí èmi náà wá bá ọ lórí omi." 29 Jésù sì ṣọ wípé, wá. Pétérù sì jáde kúrò nínú ọkọ̀, ó sìn rìn lórí omi láti lọ bá Jésù. Sùgbọ́n nígbàtí Pétérù sì wo afẹ́fẹ́, ẹ̀rù bà á. Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní rì, Ó sì kígbe pé, " Olúwa gbà mí!" 31 Lọ́gán ni Jésù na ọwọ́ rẹ̀ jáde, ó sì di Pétérù mù ú, ó sì sọ fún pé, "Ìwọ onígbàgbọ́ kékeré, ìwọ́ ṣe ṣ'iyèméjì. 32 Nígbànáà ni Jésù àti Pétérù sì wọ nú ọkọ̀, afẹ́fẹ́ náà dáwọ́ dúró. 33 Àwọn ọmọ ẹ̀yìn nínú ọkọ̀ náà sì fi orí balẹ̀ fún Jésù, wọ́n sì wípé, "Nítòótọ́ ìwọ ni ọmọ Ọlọ́run." 34 Nígbàtí wọ́n sì ti rékọjá, wọ́n dé orí ilẹ̀ Gẹ́nẹ́sárẹ́tì. 35 Nígbàtí àwọn ará ìlu náà sì mọ Jésù, wọ́n rán ṣẹ́ sí gbogbo agbègbè yíká wọn, wọ́n sì gbé gbogbo aláìlera tọ̀ ọ́ wá. 36 Wọ́n sì bẹ̀ ẹ pé kí wọn ó ṣà le fi ọwọ́ kan ìṣẹ́tí aṣọ rẹ̀: ìwọn gbogbo àwọn tí ó sì fi ọwọ́ wọn kà án, ni a mú lára dá .